Máa ṣe gudugudu méje yàyà mẹ́fà tí mo bá lè wọlé ìbò Gómìnà ìpínlẹ̀ Ogun - Iyabo Obasanjo-Bello

Iyabo Obasanjo-Bello wọ aṣọ buba APC ati gele to ba a mu nibi apero ẹgbẹ oṣelu APC niluu Abuja
Ìye àkókó tí a fi kà á: Ìṣẹ́jú 6

Iyabo Obasanjo-Bello to jẹ ọkàn lára èèkàn inú ẹgbẹ oselu APC lati ipinlẹ Ogun to wa nibi apero ẹgbẹ naa to n lọ lọwọ l'Abuja sọ pe oun yoo maa se gudu-gudu meje yaya mẹfa ti wọn ba yan oun gẹgẹ bi gomina ipinlẹ Ogun

Arabinrin Iyabo ni ẹgbẹ APC ti gbaradi fun eto idibo ọdun 2027 to ń bọ lati tun jawe olubori ninu rẹ.

Iyaafin Iyabọ Obasanjo-Bello tun parọwa fun awọn agba ẹgbẹ oselu APC lati tubọ yan n àwọn obìnrin púpọ̀ sí ipò oṣèlú káàkiri orílẹede Naijiria.

O ni eyi kì í ṣe pé yóò mú ìdọ̀gba ba awọn ọkunrin atawọn obinrin, ṣùgbọ́n yóò tún jẹ́ kí ìṣọ̀kan àti ìfọkànbalẹ̀ gbilẹ̀ nínú ètò ìṣèlú.

Iyaafin Iyabo Obasanjo-Bello ni oun ni iriri gẹgẹ bi asofin àti kọmisọna tẹlẹri ni ipinlẹ Ogun.

O tun wá gbosuba fàwọn àgbà ẹgbẹ oselu APC fun isọkan àti ifọwọsowọpọ fun eto ìdìbò abẹnu ti yoo waye l'Abuja.

Iyabo ní èyí yóò je awokọse fun àwọn ẹgbẹ́ oṣelu yòókù.

Ìṣọ̀kan ati ifọwọsowopọ lo le mu Naijiria borí iṣoro eto aabo to mẹhẹ

Ninu ọrọ tiẹ, Minisita fun eto aàbò lorílẹ̀-èdè Nàìjíríà, Christopher Musa (tí ó ti fẹ́yìntì), ti jẹ ko di mimọ pe Ààrẹ Bola Tinubu ko ni kaarẹ láti mú eto àlàáfíà àti aabo padà bọ sipo ni gbogbo ipinle to wa jake jado orilẹ ede Naijiria.

Minisita wa rọ gbogbo ọmọ Nàìjíríà pé kí wọ́n ni ssuru, kí wọ́n sì fọwọ sowọ pọ pẹlu ajọ to n mojuto eto aabo láti dojú kọ gbogbo àwọn ìṣòro to n dojukọ eto orílẹ̀-èdè yii.

Minisita náà sọ pé àwọn ìpenija tó wà níwájú orílẹ̀-èdè Naijiria bayii nílò ìfọwọ́sowọ́pọ̀ gbogbo ọmọ orílẹ̀-èdè yii.

Ọgagun fẹyinti Musa sì tẹnumọ́ pé ìdàgbàsókè, àlàáfíà àti ààbò kò lè ṣẹlẹ̀ láìsí ifọwọsowọpọ gbogbo awọn ọmọ orilẹ ede Naijiria ni tile-toko.

Kí ni kókó àpérò ẹgbẹ́ òṣèlú APC tó ń wáyé nílùú Abuja dá lé lórí?

Gbọngan Eagles Square ìlú Abuja tí wọ́n fi aṣọ alawọ pupa ati awọ ewe dara si

Oríṣun àwòrán, Tobi Sangotola

Skip podcast promotion and continue reading
Èyí ni ìkànnì Whatsapp wa

Àjáàbalẹ̀ ìròyìn BBC News Yorùbá lórí WhatsApp rẹ

Darapọ̀ mọ́ wa nibì

End of podcast promotion

Ni ọjọ Aje, ọjọ Kẹtadinlọgbọn, oṣu Kẹta ọdun 2027 ni apero ẹgbẹ oṣelu All Progressives Congress, APC nibi ti wọn ti maa ṣe eto idibo ti wọn fi maa yan awọn alaṣẹ ẹgbẹ naa.

Ni gbọngan nla Ẹagles Square to wa niluu Abuja ni apero naa ti maa waye tawọn aṣoju ẹgbẹ naa si ti n balẹ si gbọngan naa.

APC jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ẹgbẹ́ òṣèlú ti ko se fọwọrọ sẹyin lorilẹ ede Nàìjíríà, wọ́n dá ẹgbẹ oṣelu APC sílẹ̀ ní oṣù Kejì ọdún 2013 nigba ti ẹgbẹ oṣelu mẹ́rin ni parapọ lati da ẹgbẹ oselu APC silẹ.

Awọn ẹgbẹ oṣelu naa ni Action Congress of Nigeria (ACN), Congress for Progressive Change (CPC), All Nigeria Peoples Party (ANPP), àti apá kan lára All Progressives Grand Alliance (APGA).

Láti ọdún 2015 ni ẹgbẹ oselu APC ti wa lori iṣejọba lorilẹ ede Naijiria nígbà tí wọ́n jawe olubori ninu eto idibo to waye lọdun 2015 ni eyi to gbe oloogbe Muhammadu Buhari wọle gẹgẹ bi aarẹ orilẹ ede Naijiria, ki Bola Ahmed Tinubu naa to jawe olubori gẹgẹ bi aarẹ orilẹ ede Naijiria lọdun 2023.

Ki ni pataki ṣiṣe apero ẹgbẹ oṣelu APC?

Gbọngan Eagles Square ìlú Abuja tí wọ́n fi aṣọ alawọ pupa ati awọ ewe dara si

Oríṣun àwòrán, Tobi Sangotola

Nibi apero gbogbogbo ẹgbẹ oṣelu to wa kaakiri orilẹ ede Naijiria ni àwọn ọmọ ẹgbẹ́ ti máa n yan àwọn asoju ti yoo maa ṣe iṣakoso ẹgbẹ naa. Awon aṣoju ẹgbẹ ti wọn yoo yan maa n wá lati wọọdu, ijọba ibilẹ, ijọba ipinlẹ ati ní ẹkùn kọọkan to wa lorilẹ ede Naijiria.

Lara awọn ipo ti wọn maa n yan awọn aṣoju ni alága gbogbogboo (National Chairman), akọ̀wé agba (National Secretary), àtiàwọn ipò míì nínú ẹgbẹ.

Lẹyin ti igbimọ to n mojuto apero naa ba ti sayẹwo gbogbo awọn oludije to n gbero lati ipo kan tabi omiran mu tan ni wọn maa wa ṣe eto ìdìbò lati yan awọn aṣoju fun ẹgbẹ́ wọn.

Àwọn ipò ìṣàkóso wọ̀nyí ní ipa púpọ̀ lórí bí ẹgbẹ́ ṣe máa ṣètò ara rẹ̀, àti bí wọ́n ṣe máa ṣe ipolongo àti ìdíje nínú àwọn eto ìdìbò to maa waye lọjọ iwájú paapaa julọ fun eto idibo ti yoo waye lọdun 2027.

Awọn wo lo ṣeeṣe ki wọn dipo alaṣẹ ẹgbẹ oṣelu APC mu lẹyin apero yii?

  • Nentawe Yilwatda

Lati ọdun 2025 ni Nentawe Yilwatda ti wa gẹgẹ bi alaga ẹgbẹ oṣelu APC. Oun naa tun fẹ dije pada gẹgẹ bi alaga gbogbogboo fun nibi apero to n waye naa.

Lẹyin ti gomina tẹlẹ ri ni ipinlẹ Kano, Abdullahi Ganduje kọwe fipo alaga ẹgbẹ naa silẹ lọdun 2025 nitori ilera rẹ ni Yilwatda gbakoso ẹgbẹ naa.

Ohun ti a ń gbọ ni pe awọn agba inu ẹgbẹ oṣelu APC ati awọn gomina ti fẹnuko lati tun yan Nentawe Yilwatda pada gẹgẹ bi aarẹ ẹgbẹ.

  • Ajibola Basiru

Ni ọdun 2025 ni oun naa di akọwe apapọ fun APC ti ireti si wa pe oun naa fẹ pada sipo naa lẹyin apero to n lọ lọwọ naa.

  • Ali Bukar Dalori

Oun ni igbakeji alaga ẹgbẹ oselu APC lati ọdun 2025.

Ipo alaga APC ni Dalori n gbero lati dimu bayii lẹyin apero ẹgbẹ.

Ireti wa pe gbogbo awọn alaṣẹ ti wọn di ipo kan mu tabi omiran ni wọn tun dibo yan pada lati di ipo wọn mu ni igbaradi fun eto idibo gbogbogbo to maa waye lọdun 2027.

A ti gbaradi fun apero ẹgbẹ wa - Oyebanji

Gomina ipinlẹ Ekiti, Abiodun Oyebanji ti wa sọ pe gbogbo eto ti to lati jẹ ki apero ẹgbẹ oṣelu naa lọ ni irọwọ rọsẹ, ko si so eso rere,

Oyebanji to jẹ alaga igbimọ to n ṣayẹwo awọn oludije ni ẹgbẹrun mẹjo awọn aṣoju ni awọn n reti ni lati gbogbo ẹkun mẹfa to wa lorilẹ ede Naijiria nibi apero naa.